BBC News, Yorùbá - Ìròyìn
Ìròyìn tó ṣe kókó
Èèyàn 12 kú báwọn sọ́jà ṣe ju àdó olóró, àmọ́ iléeṣẹ́ ológun ní agbébọn ni àwọn pa
Onoja ni ileeṣẹ Ologun ṣe iwadii wọn daadaa ti awọn si fidi rẹ mulẹ pe awọn agbebọn n fi ilu Lukupe atawọn ilu mii ni ijọba ibilẹ Shiroro, ipinlẹ Niger ṣe ibugbe ki awọn to lọ ṣekọlu si wọn.
Àlàyé rèé lórí ohun fà á táwọn òṣìṣẹ́ tó ń pèsè omi àti ètò ọ̀gbìn ṣe gunle ìyánṣẹ́lódì
Akọroyin BBC News Yoruba wa nibi iwọde naa, to si bawọn osisẹ, alasẹ ileeẹsẹ ati awọn adari ẹgbẹ osisẹ nipinlẹ Kwara sọrọ lati mọ ohun to sokunfa iwọde naa.
Orin, Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́, Duration 1,05
Kò ṣeé má gbọ̀ọ́
Fídíò, "Eré ìdárayá ìgbátí ni mo fi ń jẹun, wọ́n ti gbá mi léti rí tí ojú mi ya, mo sojú Nàíjíríà nínú ìdíje àgbáyé", Duration 3,29
BBC News Yoruba kan si ọkunrin kan, Kabiru Adediran to n fi ere idaraya ìgbátí jẹun láti mọ bí eré ìdárayá náà ti gbajúmọ̀ sí àti ọ̀pọ̀ ewu tó rọ̀ mọ́ ọ.
Kí ló mú kí ọkọ̀ kan ré bọ́ láti orí afárá sí ìsàlẹ̀ èyí tó pa èèyàn mọ́kànlá l‘Ogun?
FRSC ṣalaye pe ọkọ Toyota kan ti nọmba rẹ jẹ GGE722KJ gbe okiti ni ẹẹmẹta ko to di pe o jabọ lati ori afara to wa.
Àlàyé rèé lórí ohun táwọn iléeṣẹ́ ìbáraẹnisọ̀rọ̀ ṣe tí ìjọba àpapọ̀ ṣe fọnmú mọ́ wọn lọ́wọ́
Ijọba ti gbe awon igbesẹ to laami-laaka fun atunṣe ikansira ẹni gẹgẹ bi Minisita eto ikansira ẹni ṣe sọ.
"Eko Bridge yóò wà ní títìpa fún àtúnṣe láti ọjọ́ Ìṣẹ́gun" -Ìjọba Eko
Eredi titipa naa bi wọn wi ni fun atunṣe, aabo ati iwadii
Èèyàn mẹ́ta tí ẹ̀yà ara pè níjà bọ́ sọ́wọ́ NDLEA fún ẹ̀sùn òògùn olóró
Femi Babafemi ti i ṣe Adari ikede ni NDLEA, ṣalaye ninu atẹjade naa pe baba agba ẹni ọgọta ọdun (60), torukọ rẹ n jẹ Romanus Nwabara, wa lara awọn akanda ẹda ti ọwọ ba fun ẹsun naa.
Ọkọ ojú omi tí wọ́n ti ṣàwárí ààrùn hantavirus balẹ̀ sí Spain, àyẹ̀wò bẹ̀rẹ̀ fáwọn èrò
Minisita feto ilera Spain, Mónica Gracía sọ pe bí wọn ṣe n ko awọn eeyan bọlẹ ninu ọkọ naa lo n lọ ni mẹsọmẹsọ amọ gbogbo awọn eeyan to wa ninu ọkọ oju omi MS Hondius ni ko ṣoju pe ohunkohun n ṣe wọn.
Lateef Adedimeji, Oboz, àtàwọn òṣèré míì tó gbàmì ẹ̀yẹ ní AMVCA 2026
Ni alẹ ọjọ Abamẹta, ọjọ Kẹsan-an, oṣu Karun-un ni ayẹyẹ naa, to jẹ ikejila iru rẹ waye ni ipinlẹ Eko nibi ti ọpọ awọn agbjumọ oṣere tiata kaakiri ilẹ Africa pejupese si.
EFCC kéde wíwá Sadiya Farouq, mínísítà tẹ́lẹ̀ fún ètò ìbojú-àánú wo aráàlú
Awọn ẹsun bii kiko owo ilu si apo ara ẹni, aṣilo ipo ati igbimọ pọ huwa ọdaran ni EFCC kede pe oun n wa Sadiya Farouq fun.
Ẹgbẹ́ NDC kéde ipò ààrẹ sí Gúúsù Naijiria ní 2027, 2031 fún Àríwá
Ikede yii waye lọjọ Abamẹta, ọjọ kẹsan-an oṣu Karun-un ọdun 2026, nibi ipade apapọ ẹgbẹ NDC to waye niluu Abuja.
Móríwú
BBC News Yorùbá ti wà lórí ìkànnì WhatsApp
Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ
Ìròyìn Àkàgbádùn
Hantavirus: Ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa àjàkálẹ̀ àrùn tuntun tó ṣẹ́yọ, àti bí o ṣe lè dáàbò bo ara rẹ
WHO sọ fun BBC pe ''iwadii kikun si n lọ lọwọ lori awọn eeyan tawọn fura si pe wọn ni arun ọhun.''
Omoyele Sowore tún fojú balé ẹjọ́ lónìí lórí ẹ̀sùn pé ó pe Ààrẹ Tinubu ní ọ̀daràn, ohun tó bá bọ̀ rèé
Ti ẹ ko ba gbagbe, adajọ yii lo ni ki agbẹjọro Sowore kunlẹ nile ẹjọ loṣu to kọja.
Wọ́n bá òkú ọmọ ọdún mọ́kànlélógún nínú yàrá l'Osun, ariwo sọ
Ọbẹ ati nnkan kan to wa ninu ike kekere kan ni wọn ba lẹgbẹẹ oloogbe naa, ṣugbọn wọn ko mọ bo ya mọjele ni abi bẹẹ kọ.
Kí ló mú Davido ṣẹ́wélé orin kíkọ fún oṣù méjì báyìí? Àlàyé rèé
Davido ṣalaye pe oun gbe igbesẹ yii lati ṣe ipolongo ibo fun Gomina Ademola Adeleke to fẹ dupo gomina ipinlẹ fun saa keji.
Egúngun tó lé obìnrin kan láì dẹ̀yìn jìyà àjẹpọ́nnulá; Obìnrin náà ṣíṣọ lójú rẹ̀ níta gbangba ló bá di ọkọ rẹ̀
Egungun ti iṣẹlẹ abuku naa kan ni wọn pe orukọ rẹ ni Omebe, a gbọ pe egungun to fẹran jagidijagan ni.
Ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa ikọ̀ ọlọ́pàá VCRU tuntun, ìdí fún ìdásílẹ̀ rẹ̀ àti iṣẹ́ àwọn ọlọ́pàá náà
Ọga ọlọpaa ṣe ifilọlẹ naa lasiko to bawọn lọgalọga ọlọpaa ṣepade pọ niluu Abuja lana ọjọ Iṣẹgun ọjọ karun un oṣu Karun un yii.
Ọba Adeyemi Adediran, Owamiran ti ìlú Esa-oke wàjà
Ninu atẹjade ti Rasheed Olawale, ẹni to jẹ agbẹnusọ fun gomina Ademola Adeleke lede lo ti fidi rẹ mulẹ pe Ọba Adeyemi Adediran, Owamiran ti iluu Esa-oke ti waja.
Bàbá Mohbad fẹ́ jogún ọmọ rẹ̀; mi ò lè fun ní ohun tó ń fẹ́ – Wumi Aloba
Wumi lo sọ ọrọ naa ninu ifọrọwerọ kan pẹlu ileeṣẹ iroyin Channels.
Kí ló fa gbas-gbos láàárín Akpabio àti Oshiomhole nílé ìgbìmọ̀ aṣòfin, àlàyé rèé
Gẹgẹ bi a ṣe gbọ, o to iṣẹju mẹwaa ti aigbọra ẹni ye to waye laaarin awọn mejeeji fi ṣẹlẹ, lẹyin naa si ni ipade ṣẹṣẹ bẹrẹ pada.
Ohun tó dùn mi jùlọ láyé lọ̀rọ̀ tí ìyàwó mi sọ pé méjì nínú ọmọ márùn ún tí mo ṣe súná wọn kìí ṣe tèmi - Òṣèré tíátà, Tioruju
Nigba to n sọrọ ninu ifọrọwanilẹnuwo to ṣe pẹlu African A List, Tioruju ṣalaye bi o ti pada sile lati ibi to ti lọ ṣe ere ori itage, ti ko si ba iyawo rẹ ti oyun ọmọ karun un wọn wa ninu rẹ.
Ọkùnrin méje tó ṣe pàṣí-pààrọ̀ ìyàwó bọ́ sọ́wọ́ àwọn ọlọ́pàá Hisbah
Ẹka Hisbah ipinlẹ Bauchi ṣalaye pe agbegbe Azare, nijọba ibilẹ Katagum, ni ọwọ ti ba awọn baale ile meje ti wọn ni wọn n paarọ iyawo naa.
A ò tíì wẹ̀ láti ọjọ́ mẹ́ta, kò sí ìná, kò sí omi – Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ fásitì Ibadan figbe ta
Eredi ifọhẹhonuhan naa ko ṣẹyin inira wọn lẹyin iyanṣẹlodi awọn oṣiṣẹ ti kii ṣe olukọni, NASU, ninu ile ẹkọ ọhun to n lọ lọwọ.
Ìròyìn Pàtàkì
Kọ́milẹ́kọ̀ọ́
Ẹ tẹ̀lé wa lórí ìkànnì ayélujára
Ìwádìí kíkún lóríi kókó ìròyìn
Sisi Alagbo bẹ àwọn abiyamọ ayé àti ẹgbẹ́ alágbo, ó ní òun ti ṣe àṣìṣe ńlá
Ninu fidio mii to tun fi lede loju opo Facebook rẹ lọjọ Aje ọsẹ yii ni Sisi Alagbo ti kunlẹ to si n wa ẹkun mu bo ṣe n bẹbẹ fun aforiji lọwọ awọn ololufẹ rẹ, mọlẹbi rẹ atawọn ọmọ Naijiria.
Ọkùnrin tí wọ́n sinòkú rẹ padà wọ ìlú, ariwo sọ
Ileeṣẹ iroyin Daily Monitor jabọ pe, Godwin Baguma, lati ilu Kijana to wa lagbegbe Kijura ni Uganda ti di awati fun ọpọlọpọ ọsẹ, eyii to sọ awọn mọlẹbi rẹ sinu iporuru.
Àwọn ajínigbé tún jí òṣìṣẹ́ iléeṣẹ́ iná mọ̀nàmọ́ná IBEDC gbé, àwọn aláṣẹ ké gbàjarè síta
Iroyin sọ pe ẹkun ileeṣẹ mọnamọna IBEDC ni ipinlẹ Ogun lawọn oṣiṣẹ mejeeji yii ti n ṣiṣẹ ki wọn to ko sọwọ awọn afurasi ajinigbe naa.
Èmi ò sọ̀rọ̀ tàbùkù Olubadan o, ọmọ ni mo jẹ́ sí Ọba Rashidi Ladọja - Bayọ Adelabu sọ̀rọ̀ síta lẹ́yìn tí wọ́n ní ó sọ̀kò ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ s'Olubadan nítorí òṣèlú
Adelabu ni irọ to jina si otitọ ni ohun tawọn eeyan nsọ, ati pe ara ọna lati pagidina igbesẹ oṣelu oun ni.
"Ọlọ́pàá Kwara ti ọmọ mi obìnrin ọmọ ọdún 16 mọ́lé láìṣẹ̀, wọ́n ni ó gbọdọ̀ ṣẹ̀wọ̀n"
Ninu fidio kan to n mi igboro titi loju opo X ni obinrin naa ti fẹsun kan ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Kwara pe wọn mu ọmọ naa dipo ẹgbọn rẹ ti wọn fẹsun ole jija kan lẹyin ti ẹgbọn rẹ to jẹ afurasi na papa bora.
'Mi ò lè sọ bí inú mi ṣe dùn tó,' Lateef Adedimeji sọ̀rọ̀ lórí ọmọkùnrin mẹ́ta tí Elédùà fi ta ẹbí rẹ̀ lọ́rẹ
Lateef Adedimeji sọ loju opo Facebook rẹ wi pe ''awọn eeyan ti fi ifẹ nla han si wa, o si jẹ nnkan to dara gan an.''
Ǹ jẹ́ o mọ̀ pé fítámì tó lè ṣe ara rẹ lóore wà nínú ọtí? Àlàyé rèé
Fitami ọhun ti wọn n pe ni B6 ni iwadii naa sọ pe o dara fun ọpọlọ ati ẹjẹ, o si tun maa n koju aisan to ba fẹ wọ inu agọ ara.











































































